Ẹgbẹ́ òṣèlú Adeleke àti Oriyomi fapá jánú lẹ́yìn tí ilé ẹjọ́ ní kí INEC yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ rẹ̀

📌 Diğer 📰 Nigeria 🕐 3 saat önce
Ẹgbẹ́ òṣèlú Adeleke àti Oriyomi fapá jánú lẹ́yìn tí ilé ẹjọ́ ní kí INEC yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ rẹ̀

Ẹwẹ, ẹgbẹ oṣelu ADC to jẹ ẹgbẹ Atiku Abubakar ti sọ pe ile ẹjọ fẹ lo ara rẹ lati ṣakoba fun ijọba awaarawa pẹlu idajọ ti ileẹjọ apapo l'Abuja gbe jade.

Ẹgbẹ oṣelu ADC ati Accrod ti bu ẹnu atẹ lu idajọ ile ẹjọ giga kan niluu Abuja to ni ki ajọ eleto idibo, INEC, fa orukọ awọn ẹgbẹ oṣelu naa yọ ninu akọsilẹ rẹ nitori wọn ko ba ofin mu.

Lara awọn to bu ẹnu atẹ lu idajọ naa ni gomina Ademola Adeleke ti ipinlẹ Osun to juwe idajọ ọhun gẹgẹ bii aṣilo ẹka eto idajọ ni Naijiria.

O ni ko si ohun ti yoo yẹ kikopa ẹgbẹ oṣelu Accord ninu eto idibo gomina ti yoo waye ninu oṣu Kejọ ọdun yii ni ipinlẹ naa.

Ẹgbẹ awọn aṣofin nigba kan ri, National Forum of Former Legislators, lo pe ẹjọ naa lati bere lọwọ ile ẹjọ pe ṣe INEC lẹtọọ lati wọgile awọn ẹgbẹ oṣelu ti wọn kuna lati ni awọn amuyẹ to wa ni abala 225A ti ofin ọdun 1999, eyii ti wọn ṣatunṣe rẹ lọdun 2022.

Nigba ti awọn alakoso ẹgbẹ Accord yoo sọrọ, wọn ni idajọ naa ko ba ofin mu latari pe o tako idajọ ile ẹjọ kotẹmilọrun to ti waye ṣaaju.

Accord ni idajọ ọhun waye bo tilẹ jẹ pe idajọ kan ti waye ṣaaju, eyii to tako idajọ ile ẹjọ giga tuntun yii.

Ẹgbẹ oṣelu naa fi kun pe awọn ti bẹrẹ igbeṣe lati pe idajọ naa nija nile ẹjọ laipẹ.

Accord ni idajọ ọhun ko fo oun laya nitori oun jawe olubori ninu eto idibo sipo kansẹlọ to waye ni Jigawa lẹnu lọlọ yii.

Lẹyin naa ni wọn ni ki awọn ọmọ ẹgbẹ naa atawọ alatilẹyin awọn ma foya nitori wọn yoo kopa ninu eto idibo sipo gomina ipinlẹ Ekiti ati ti ipinlẹ Osun to n bọ laipẹ yii.

Ofin wo gan ni ile ẹjọ sọ pe awọn ẹgbẹ oṣelu ọhun tẹ loju mọlẹ?

Gẹge bii ohun ti adajọ to gbọ ẹjọ ọhun, Peter Lifu sọ, awọn ẹgbẹ oṣelu naa kọlu abala 225A ti ofin ọdun 1999 eyii ti wọn ti ṣe atunṣe si.

Gẹgẹ bii ohun ti awọn to pe ẹjọ ọhun sọ, awọn ẹgbẹ oṣelu naa kuna lati ni awọn amuyẹ naa ninu awọn eto idibo to waye lẹnu lọlọ yii.

Ile ẹjọ ti wa paṣẹ ki INEC yọ orukọ awọn ẹgbẹ oṣelu naa kuro ninu iwe rẹ, o tun paṣẹ ki INEC ma jẹ ki wọn kopa ninu eto idibo ọjọ iwaju bii eto idibo to n bọ lọdun 2027.

Ile ẹjọ giga apapọ niluu Abuja ti paṣẹ fun ajọ eleto idibo INEC pe ko yọ orukọ ẹgbẹ oṣelu ADC, Accord ati ẹgbẹ oṣelu mẹta mii kuro ninu awọn ẹgbẹ ti yoo kopa ninu eto idibo 2027 to n bọ.

Awọn ẹgbẹ oṣelu mẹta toku ni ẹgbẹ APP, ẹgbẹ oṣelu AA, ati ẹgbẹ ZLP.

Adajọ Peter Lifu lo paṣẹ naa nile ẹjọ giga apapọ l'Abuja lọjọ Aje ọjọ kẹẹdogun oṣu Kẹfa yii.

Ṣaaju ni igbimọ awọn aṣofin tẹlẹri ti beere pe ki ile ẹjọ sọ boya ajọ eleto idibo INEC lagbara labẹ ofin lati yọ awọn ẹgbẹ oṣelu to ba kuna lati ṣe nnkan ti abala 225A iwe ofin orilẹede Naijiria sọ kuro, eyi to wa ni ibamu pẹlu atunṣe ofin eto idibo Naijiria ti ọdun 2022.

Igbimo awọn aṣofin tẹlẹri naa sọ fun ile ẹjọ wi pe awọn ẹgbẹ oṣelu marun un yii ti kuna lati maa tẹsiwaju gẹgẹ bii ẹgbẹ oṣelu ni Naijiria

📌 Kaynak

Bu haber XML kaynağından derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.

Orijinal haberi oku →
📱
News AI World — Mobil uygulama
Bu haberleri 45 dilde, anlık çeviriyle cebinde. Erken erişim için Gmail adresini bırak.
← Tüm haberlere dön