Ìdí tí ilé ẹjọ́ kòtẹ́milọ́rùn fi ṣẹ́wélé àṣẹ adájọ́ tó ní kí INEC yọ orúkọ ẹgbẹ́ òṣèlú Oriyomi, Adeleke àti Atiku kúrò nínú àkọsílẹ̀ rẹ̀
Igbimọ adajọ ẹlẹni mẹta ti Adajọ A. B. Mohammed dari bu ẹnu ẹtẹ lu bi Adajọ Peter Lifu ile ẹjọ giga apapọ l'Abuja ṣe dajo tako aṣẹ ile ẹjọ to jade lọjọ kejilelogun oṣu Karun un to kọja; eyi to sọ pe ko gbọdọ gbe igbesẹ lori ẹjọ to wa niwaju rẹ.
Oríṣun àwòrán, Oriyomi Hamzat/X/Atiku Abubakar/X/Ademola Adeleke/X
Ilẹ ẹjọ kotẹmilọrun ti ṣẹwele aṣẹ ile ẹjọ giga apapọ l'Abuja to ni ki ajọ eleto idibo INEC yọ orukọ ẹgbẹ oṣelu ADC, Accord, ZLP, AA ati APP kuro ninu awọn ẹgbẹ ti yoo kopa ninu eto idibo to n bọ.
Igbimọ adajọ ẹlẹni mẹta ti Adajọ A. B. Mohammed dari bu ẹnu ẹtẹ lu bi Adajọ Peter Lifu ile ẹjọ giga apapọ l'Abuja ṣe dajo tako aṣẹ ile ẹjọ to jade lọjọ kejilelogun oṣu Karun un to kọja; eyi to sọ pe ko gbọdọ gbe igbesẹ lori ẹjọ to wa niwaju rẹ.
Awọn adajọ mẹtẹẹta naa sọ pe iwa to tako eto idajọ ni Adajọ Lifu hu pẹlu idajọ ti o gbe kalẹ.
Igbimọ oludajọ naa ni nnkan ti Adajọ Lifu ṣe tako ilana eto idajọ ati iwe ofin orilẹede Naijiria ti ọdun 1999.
''Igbesẹ ile ẹjọ giga lati gbe idajọ kalẹ lẹyin ti ile ẹjọ kotẹmilọrun ti paṣẹ idaduro lori ọrọ naa jẹ iwa to ko kudiẹ kaato eyi to lodi si ilana eto idajọ.
Koda, ile ẹjọ to ga julọ ni Naijiria ti sọ pe iru adajọ to ba huwa bayii ko yẹ lati maa ṣiṣẹ adajọ tori iwa jagidijagan ni eleyii tumọ si ninu eto idajọ.
Ile ẹjọ ni lati maa gbiyanju ki orukọ wọn ma bajẹ, ile ẹjọ kotẹmilọrun ni aṣẹ lori nnkan ti ile ẹjọ giga ba n ṣe lori ọrọ to ba wa niwaju rẹ.
Ile ẹjọ kotẹmilọrun si le paṣẹ lati ri wi pe gbogbo nnkan lọ ni ibamu pẹlu alakalẹ ofin.
Idi niyii ti ile ẹjọ yii fi ṣẹwele aṣẹ ile ẹjọ giga apapọ to ni ki ajọ INEC yọ orukọ ẹgbẹ oṣelu marun un kuro ninu akọsilẹ rẹ,'' igbimọ oludajọ ṣalaye.
Ṣaaju ni ajọ eleto idibo INEC funra rẹ ti sọ fun ile ẹjọ wi pe idajọ ti Adajọ Lifu gbe kalẹ jẹ iyalẹnu foun.
Koda, INEC tun sọ pe ninu iwe iroyin loun ti ri iroyin naa ka tori ile ẹjọ giga ko sọ nnkan foun nipa idajọ naa.
Ajọ eleto idibo Naijiria ni oun mọ nipa aṣẹ ile ẹjọ to jade lọjọ kejilelogun oṣu Karun un, eyi to ni ile ẹjọ giga ko gbọdọ tii gbe idajọ kalẹ lori ọrọ to wa niwaju rẹ bayii.
Ni bayii, orukọ ẹgbẹ oṣelu maraarun un ADC, Accord, ZLP, AA ati APP tọrọ kan si wa ni akọsilẹ INEC titi ti igbẹjọ ẹjọ kotẹmilọrun ti wọn pe yoo fi waye.
Ẹgbẹ oṣelu ADC ati Accrod ti bu ẹnu atẹ lu idajọ ile ẹjọ giga kan niluu Abuja to ni ki ajọ eleto idibo, INEC, fa orukọ awọn ẹgbẹ oṣelu naa yọ ninu akọsilẹ rẹ nitori wọn ko ba ofin mu.
Lara awọn to bu ẹnu atẹ lu idajọ naa ni gomina Ademola Adeleke ti ipinlẹ Osun to juwe idajọ ọhun gẹgẹ bii aṣilo ẹka eto idajọ ni Naijiria.
O ni ko si ohun ti yoo yẹ kikopa ẹgbẹ oṣelu Accord ninu eto idibo gomina ti yoo waye ninu oṣu Kejọ ọdun yii ni ipinlẹ naa.
Ẹgbẹ awọn aṣofin nigba kan ri, National Forum of Former Legislators, lo pe ẹjọ naa lati bere lọwọ ile ẹjọ pe ṣe INEC lẹtọọ lati wọgile awọn ẹgbẹ oṣelu ti wọn kuna lati ni awọn amuyẹ
📌 Kaynak
Bu haber XML kaynağından derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.
Orijinal haberi oku →