Ṣé lóòótọ́ ni ìjọba àpapọ̀ ti sanwó ìjọba ìbílẹ̀ Osun tó dẹjọ́? Àlàyé rèé

📌 Diğer 📰 Nigeria 🕐 4 saat önce
Ṣé lóòótọ́ ni ìjọba àpapọ̀ ti sanwó ìjọba ìbílẹ̀ Osun tó dẹjọ́? Àlàyé rèé

Ọpọ igba ni gomina naa ti sọ pe owo ara oun loun fi n sanwo fawọn oṣiṣẹ to wa labẹ ijọba ibilẹ, latigba ti ijọba apapọ ko ti i sanwo naa si aaye to yẹ.

Awuyewuye lori owo awọn ijọba ibilẹ nipinlẹ Osun ti n waye tipẹ, pẹlu bi ijọba apapọ ko ṣe sanwo naa si asunwon ti Gomina Ademola Adeleke n fẹ labẹ ofin.

Ọpọ igba ni gomina naa ti sọ pe owo ara oun loun fi n sanwo fawọn oṣiṣẹ to wa labẹ ijọba ibilẹ, latigba ti ijọba apapọ ko ti i sanwo naa si aaye to yẹ.

Ẹ o ranti pe ọrọ bẹrẹ si I fẹju lorii ta lo yẹ nipo awọn olori kansu ninu awọn PDP igba naa atawọn APC ti ijọba apapọ tilẹyin.

Ọrọ naa pada de kootu, o si di ohun ti ile ẹjọ da, pe o lodi fun ijọba apapọ lati gbẹsẹ le owo ijọba ibilẹ l'Osun.

Amọ lẹnu ojo meloo kan yii ni iroyin bẹrẹ si i jade, pe ijọba apapọ ti sanwo naa si asunwọn ti Adeleke n fẹ.

Eyi kọ ni igba akọkọ ti iroyin yoo jade bẹẹ amọ ti yoo pada ja si irọ.

Lati mọ otitọ to wa nidii ọrọ naa lọtẹ yii, BBC Yoruba kan si ijọba ipinlẹ Osun lati ṣalaye, Agbẹnusọ fun Gomina Adeleke, iyẹn Olawale Rasheed si ṣalaye pe:

Nigba to n ṣalaye ọrọ naa laaarọ Ọjọru, ọjọ kẹtadinlogun oṣu Kẹfa ọdun 2026 yii, Agbẹnusọ Gomina Osun naa sọ pe:

"Nnkan to ṣẹlẹ nipa owo kansu ni pe ijọba apapọ ni awọn ti san an, wọn wa ni pe ko sohun to kan awọn mọ.

"Ṣugbọn akanti to yẹ ki wọn sanwo si ni eyi ti ijọba ipinlẹ ba fi lelẹ labẹ ofin, awọn eeyan naa ni yoo jẹ ẹni to le gba owo jade, awọn bii olootu eto inawo ipinlẹ ati bẹẹ bẹẹ lọ.

" Ofin ipinlẹ wa lo sọ bẹẹ, awọn to yẹ ki wọn ṣi akanti naa labẹ ofin niyẹn.

"Ṣugbọn nigba ti UBA fẹẹ ṣi akanti, ayederu ni wọn lọ gba lọdọ awọn alaga 'Yes or No'.

" Awọn alaga ti mo n pe bayii ni awọn alaga ti kootu ti le pe wọn ko lẹtọọ lati wa nipo mọ, amọ ti wọn ṣaa yari, ti wọn joye Akintola taku pe awọn ko lọ.

"Eyi ni ijọba ipinlẹ Osun ṣe gbe UBA lọ si kootu, pe akanti ti ko ba ofin mu ni won sanwo si, ọwọ ijọba Adeleke ko to owo naa.Enikẹni to ba si fọwọ kan owo naa lati ita, o le lo ja, owo olowo lo na.

Gẹgẹ bi Olawale Rasheed ṣe ṣalaye lorukọ ijọba Osun, o ni ijọba apapọ ti sanwo, ṣugbọn UBA n ṣe apade alude laaarin rẹ pẹlu awọn alaga ti kootu ti le lọ.

"UBA naa pada lọ si kootu, pe awon ko na owo yẹn, o wa nibẹ, ati pe awọn tọrọ kan kọwọ bọwe, owo naa le ni 300b.

"Ijọba ipinlẹ Osun gba pe irọ ni wọn n pa, nigba ti ile ẹjọ ti ni awọn alaga yẹn ko lẹsẹ nilẹ, ohun to yẹ ki wọn ṣe ni ki wọn pe awọn eeyan ti ofin fọwọ si lati jẹ alakooso, ki wọn le mọ nipa rẹ.

"Awọn bii Olootu inawo ipinlẹ Osun, Olootu ẹka iṣejọba, lo yẹ ki wọn ṣi akanti yẹn, wọn a le maa sanwo awọn tiṣa atawọn mi-in to ba tun lẹtọọ si i."

Agbẹnusọ Gomina Adeleke naa sọ pe nigba ti wọn ko jẹ ko ri bẹẹ ni Adeleke ṣe n sanwo awon tiṣa, awọn oṣiṣẹ eleto ilera abẹle, oṣiṣẹfẹyinti atawọn mi-un lati bii ọdun kan

📌 Kaynak

Bu haber XML kaynağından derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.

Orijinal haberi oku →
📱
News AI World — Mobil uygulama
Bu haberleri 45 dilde, anlık çeviriyle cebinde. Erken erişim için Gmail adresini bırak.
← Tüm haberlere dön