Inú gbogbo èèyàn ìpínlẹ̀ Osun ló dún sí ìdájọ́ tó fààyè gba Accord láti díje, Adeleke ní wọ́n ń fẹ́ - Ìjọba Osun

📌 Diğer 📰 Nigeria 🕐 3 saat önce
Inú gbogbo èèyàn ìpínlẹ̀ Osun ló dún sí ìdájọ́ tó fààyè gba Accord láti díje, Adeleke ní wọ́n ń fẹ́ - Ìjọba Osun

Agbẹnusọ fun Gomina Ademola Adeleke, Olawale Rasheed to ba BBC News Yoruba sọrọ lori idajọ naa sọ pe ki i ṣe gomina nikan ni idajọ ọhun dun mọ, bi ko ṣe gbogbo ọmọ ipinlẹ Osun pata.

Lẹyin ti ile ẹjọ Kotẹmilọrun ti paṣẹ pe ẹgbẹ oṣelu Accord atawọn yooku ti ile ẹjọ giga sọ pe wọn ko le dije ninu idibo to n bọ yii yoo kopa, ijọba ipinlẹ Osun ti sọ ero ọkan rẹ lori idajọ naa ati igbese to kan.

Agbẹnusọ fun Gomina Ademola Adeleke, Olawale Rasheed to ba BBC News Yoruba sọrọ lori idajọ naa sọ pe ki i ṣe gomina nikan ni idajọ ọhun dun mọ, bi ko ṣe gbogbo ọmọ ipinlẹ Osun pata.

"Idajọ akọkọ yẹn ko ba ofin Naijiria mu,idajọ abẹ ile ni. Ikeji ni pe o tun tapa si idajọ to ti wa nilẹ nile ẹjọ to tun ga . Gbogbo wa l'Osun ti mọ pe irọ ni."

O ni eyi ni Gomina ṣe fi atẹjade sita, pe ki araalu fi ọkan balẹ, ki wọn ma ṣe ja, nitori orukọ Accord yoo wa lori iwe idibo loṣu Kẹjọ ti idibo yoo waye.

"Mo fẹẹ fi da yin loju pe ki i ṣe Gomina nikan ni inu wọn dun si idajọ ile ẹjọ Kotẹmilọrun, gbogbo eeyan ipinlẹ Osun ni inu wọn dun si i."

Agbẹnusọ gomina naa fi kun alaye rẹ pe ọpọ eeyan lo fẹran Gomina Adeleke, ti wọn si fẹ ko jẹ pe oun ni yoo maa tẹsiwaju nipo rẹ.

"Araalu fẹran Adeleke, oun ni wọn fẹ ko maa tẹsiwaju ninu iṣejọba Osun."

Olawale fi kun un alaye rẹ pe ikọ ipolongo ibo fun Gomina Adeleke ti bẹrẹ ikede naa lọjọ Iṣẹgun ọsẹ yii, nibi ti Gomina funra rẹ ti kede awọn erongba rẹ.

"Ọjọ kẹẹẹdogun, oṣu Kẹjọ ni idibo yoo waye. Accord yoo wa nibẹ lati dije, araalu yoo si wa nibẹ lati dibo fun ẹni ti wọn fẹ."

O fi kun un pe ero rẹpẹtẹ lo wa nibi eto naa, eyi to fi han pe gomina Adeleke ni awọn eeyan Osun n fẹ bo ṣe sọ.

Gẹgẹ bi Agbẹnusọ Gomina Osun naa ṣe wi lori igbesẹ ti wọn yoo maa gbe bi ọrọ yii ṣe n lọ, o ni ijọba ti ko fẹran janduku ni ijọba Gomina Adeleke.

O fi kun un pe ko sohun to le ṣẹlẹ, ile ẹjọ ni Gomina Adeleke yoo maa lọ lati yanju ọrọ.

" A ko ni i huwa janduku kankan, ijọba to fẹran alaafia ni ti Gomina Ademola Adeleke, ile ẹjọ ni a o maa gbe ohun gbogbo lọ lati yanju.

"Ofin la o fi yanju gbogbo ohun to ba ku, a tun maa waa fibo yanju ẹ lọjọ kẹẹẹdogun oṣu Kẹjọ, kawọn eeyan lọ dibo fun ẹni to ba wu wọn.

" Ko nilo kawọn eeyan maa yinbọn tabi ki wọn maa ja, iwe idibo yoo wa lọwọ ẹnikọọkan, ki wọn lọ dibo fun ẹni to ba wu wọn."

Awuyewuye lori owo awọn ijọba ibilẹ nipinlẹ Osun ti n waye tipẹ, pẹlu bi ijọba apapọ ko ṣe sanwo naa si asunwon ti Gomina Ademola Adeleke n fẹ labẹ ofin.

Ọpọ igba ni gomina naa ti sọ pe owo ara oun loun fi n sanwo fawọn oṣiṣẹ to wa labẹ ijọba ibilẹ, latigba ti ijọba apapọ ko ti i sanwo naa si aaye to yẹ.

Ẹ o ranti pe ọrọ bẹrẹ si I fẹju lorii ta lo yẹ nipo awọn olori kansu ninu awọn PDP igba naa atawọn APC ti ijọba apapọ tilẹyin.

Ọrọ naa pada de kootu, o si di ohun ti ile ẹjọ da, pe o lodi fun ijọba apapọ l

📌 Kaynak

Bu haber XML kaynağından derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.

Orijinal haberi oku →
📱
News AI World — Mobil uygulama
Bu haberleri 45 dilde, anlık çeviriyle cebinde. Erken erişim için Gmail adresini bırak.
← Tüm haberlere dön