Wo kókó ohun méje tí Tinubu sọ, bó ṣe pàṣẹ kí ICPC bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí Adeniyi Adeyemi àti ìdásílẹ̀ ayédèrú iléeṣẹ́ ìjọba
Agbẹnusọ Aarẹ, Bayo Onanuga, sọ ninu atẹjade kan pe Aarẹ ni oun gbọdọ gba esi abajade iwadii naa laarin ọgbọn ọjọ ọhun.
Ni ọjọ Isẹgun ni iroyin gbalẹ kan pe ileesẹ ọlọpaa ilẹ wa ti lọ gbe Baba Adeniyi Adeyemi, ti ileesẹ aarẹ fẹsun kan pe o da ayederu ileesẹ silẹ eyi to so mọ ileesẹ aarẹ.
Iroyin naa ni lẹyin ti Adeniyi Adeyemi di awati, ni ileeṣẹ ọlọpaa nawọ gan baba rẹ, alagba Adetunji Adeniyi.
Ọjọ Aje ni iroyin naa sọ pe awọn ọlọpaa gbe baba naa nile rẹ nilu Ogbomoso.
Idi ree ti BBC News Yoruba fi morile ilu Ogbomoso lati mọ bi wọn se mu baba naa, ka si bawọn eeyan ti isẹlẹ naa soju wọn sọrọ.
Amọ iyalẹnu lo jẹ fun wa pe awọn ọlọpaa ti fi baba naa silẹ lẹyin wakati diẹ ti wọn gbe e, to si ti wa ninu ile rẹ nilu Ogbomoso.
Alagba Adetunji Adeniyi wa ba BBC News Yoruba sọrọ nipa ohun to la kọja lọwọ ọlọpaa ati ohun to mọ nipa ọmọ rẹ.
Nigba to n ba BBC News Yoruba sọrọ, alagba Adetunji Adeyemi ni ogiri fẹnsi ile oun ni awọn ọlọpaa gba wọle sinu ile naa.
Adetunji Adeniyi ni "Gbogbo irin babu waya ti a fi yi ogiri ile po ati ilẹkun ọna mi ni wọn bajẹ, ti wọn fi gba fẹnsi wọle.
Mo beere wi pe lati ibo ni wọn ti wa, wọn si sọ pe ẹṣọ alaabo ni awọn jẹ.
Mo sọ pe n ko ni sikiọriti nile, ṣugbọn wọn sọ pe sikiọriti ijọba ni awọn, eyi lo jẹ ki n ṣilẹkun fun wọn."
Alagba Adetunji tẹsiwaju pe bi oun ṣe ṣilẹkun fun wọn tan, loju ẹsẹ ni gbogbo wọn ti da wọle.
O ni gbogbo inu ile oun ni wọn yẹwo, titi kan gbogbo inu ibi ti oun n ko aṣọ si ati ile idana ni wọn yẹwo.
Adeniyi fikun pe nigba to ya ni wọn lọ, iyẹn ni nnkan bi agogo kan ọsan.
Sugbọn nigba to tun di bi agogo meji aabọ, wọn tun pada wa, wọn si ko foonu wa, ko to di pe wọn tun lọ.
"Nigba to di nnkan bi agogo mọkanla aabọ ni aarọ, bi wọn tun ṣe de niyẹn.
Koda bi eeyan ba gbe ṣigidi min, bawo ni ọkan ko ṣe ni mi soke, wi pe ewo tun leleyi, iwọ Ọlọrun mi.
Ninu ifọrọwerọ pẹlu baba Adeniyi, BBC News Yoruba beere lọwọ rẹ nipa ọmọ rẹ, Adeniyi Adeyemi ati isẹ to n se.
Baba naa fesi pe awọn ọlọpaa naa beere ibeere ọhun lọwọ ohun, gẹgẹ bi awa naa ti beere.
Wọn beere pe nibo lo ti n ṣiṣẹ, mo sọ pe n ko mọ, ṣugbọn abẹ ijọba lo loun wa.
Ọmọ mi kii ṣe ẹni to laapọn, bẹẹ si ni kii ṣe onijọgbọn eeyan, ṣugbọn mo mọ pe o n ṣiṣẹ l'Abuja, labẹ ijọba si lo sọ pe oun ti n ṣiṣẹ.
Kii ṣe onijọgbọn, kii ba eeyan jẹ lati kekere rẹ, titi to fi de ibi to de lonii.
Ara mi ko da, gbogbo ohun ti mo n gbọ pẹlu rumọọsi ti wọn wa n fun mi, ko dun mọ mi ninu.
O jọ mi loju, ko si ye mi di akoko yii gan-an, bi mo ba sọ pe o ye mi, irọ ni mo pa.
Adetunji Adeniyi tun si asọ loju rẹ fun BBC News Yoruba pe ọmọ oun wa sile ni ọjọ Isẹgun ọsẹ to kọja, to si pada silu Abuja ni ọjọ keji.
"Nigba to di ni ana, wọn bẹrẹ sii beere lọwọ mi pe bawo ni emi ko ṣe
📌 Kaynak
Bu haber XML kaynağından derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.
Orijinal haberi oku →