Wàhálà bẹ́ sílẹ̀ láàárín àwọn Yorùbá àti Huasa ní Ibadan, èèyàn mẹ́ta jáde láyé

📌 Diğer 📰 Nigeria 🕐 2 saat önce
Wàhálà bẹ́ sílẹ̀ láàárín àwọn Yorùbá àti Huasa ní Ibadan, èèyàn mẹ́ta jáde láyé

Gẹgẹ bi iroyin to tẹ wa lọwọ, nnkan bii aago mẹsan-an alẹ ojọ Iṣẹgun ni iṣẹlẹ naa waye laaarin ọkunrin to jẹ Yoruba to n wa kẹkẹ ẹlẹsẹ mẹta ti ọpọ eeyan mọ si maruwa ati awọn Hausa ti wọn maa n ṣa irin aloku ta.

Niṣe ni ọrọ di eni ori yọ o dile ni agbegbe Ojoo ni ilu Ibadan, olu ilu ipinlẹ Oyo nigba ti ija nla kan bẹ silẹ laaarin awọn Yoruba atawọn Hausa to wa ni agbegbe naa.

Gẹgẹ bi iroyin to tẹ wa lọwọ, nnkan bii aago mẹsan-an alẹ ojọ Iṣẹgun ni iṣẹlẹ naa waye laaarin ọkunrin to jẹ Yoruba to n wa kẹkẹ ẹlẹsẹ mẹta ti ọpọ eeyan mọ si maruwa ati awọn Hausa ti wọn maa n ṣa irin aloku ta.

Iroyin sọ pe ija naa tun tẹsiwaju ni owurọ yii ko to di pe awọn ẹṣọ aabo tete ji giri si ko ma ba a di wahala ẹlẹyamẹya laaarin awọn ti ija naa ti waye.

Ni owurọ ọjọru ni awọn ọdọ ti inu n bi di gbogbo opopona to wa ni agbegbe naa, ti wọn si ẹnikẹni ko ni gba ọna naa kọja.

Eyi fa sunkẹrẹ fakẹrẹ ọkọ bi awọn eeyan ko ṣe ri bi kọja ni agbegbe naa ṣugbọn ti wọn pada ṣi ọna leyin ti igbakeji gomina ipinlẹ Oyo ṣabewo si agbegbe naa.

Nigba ti BBC News Yoruba kan si agbegbe Ojoo, ijọba ibilẹ Akinyele ti iṣẹlẹ naa ti waye ṣalaye ohun to ṣẹlẹ ni pato fun wa.

Awọn ọdọ ti inu n bi naa ṣalaye pe ọkunrin to n wa kẹkẹ naa lọ ra ounjẹ noodles lọwọ ọkunrin Hausa to n ta noodles ni agbegbe naa ti o fẹ jẹ ni alẹ ana.

O ni lẹyin to jeun tan lo fi owo ranṣẹ si Hausa naa lati ori foonu ṣugbọn ti Hausa to n ta noodles naa sọ pe oun ko ri owo naa.

Wọn sọ pe eti lo bẹrẹ ifanfa laaarin awọn mejeeji ko to di pe awọn Hausa mii ni agbegbe dide si wọn, ti wọn si bẹrẹ si ni lu ọkunrin Yoruba naa, fi nnkan gun-un titi ti ẹmi fi bọ lọrun rẹ.

Wọn ni eyi lo mu ki awọn Yoruba to w ani agbegbe naa dide lati gbeja eeyan wọn ti wọn pa, ti ọrọ naa si di wahala nla, ti wọn fi sọ ina si agbegbe tawọn Hausa naa n lo lati ṣe ọja awọn nnkan ti wọn n ṣa.

Nigba to n ba igbakeji gomina ipinlẹ Oyo, Adebayo Lawal, to ṣabẹwo si agbegbe naa ni owurọ yii sọrọ, ọkan lara awọn aṣoju ọdọ ni agbegbe naa, Olamiposi Azeez sọ pe igba akọkọ kọ niyii ti iru wahala bayii ti maa n ṣẹlẹ ni agbegbe Akinyẹle.

Olamiposi salaye pe awọn Hawusa ti wọn wa ni ori oke Ọjọọ ni awọn ohun kan ija oloro lowo eyi ti wọn lo lati fi gbẹmi eeyan mẹta.

O ni lati ori oke ti wọn wa ni wọn ti n yin ibọn si awọn eniyan ti wọn wa ni titi.

O beere pe ki ijọba wa ọna ti wọn fi maa ko awọn Hausa ti wọn n gbe ni ori oke naa kuro nitori wahala to maa n waye lemọlemọ ni agbegbe naa ati pe o ṣeeṣe ki wahala mii tun be silẹ ti awọn ọdọ ti inu n bi lori iṣẹlẹ naa ba tun lọ ṣe ikọlu si wọn.

Ninu ọrọ rẹ, igbakeji Gomina ipinlẹ Oyo, Amofin Abdulraheem Adebayo Lawal sọ pẹ nnkan ibanujẹ ni ohun to ṣẹlẹ ni alẹ ọjọ Iṣẹgun mọjumọ naa to si le tapo aala si ipinlẹ Oyo.

O rọ awọn ọdọ lati ṣe suuru lori iṣẹlẹ naa, pe ijọba ti gbọ si iṣẹlẹ naa, ti wọn si maa gbe igbesẹ akin l

📌 Kaynak

Bu haber XML kaynağından derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.

Orijinal haberi oku →
📱
News AI World — Mobil uygulama
Bu haberleri 45 dilde, anlık çeviriyle cebinde. Erken erişim için Gmail adresini bırak.
← Tüm haberlere dön