Oriyomi Hamzat ṣàlàyé àjọsẹpọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú Sheikh Gumi, ìgbésùnmọ̀mí àti akatakítí ẹ̀sìn
Ni itẹsiwaju alaye rẹ, Oriyomi Hamzat sọ pe oun ko ṣalaye ọrọ yii nitori ki araalu le dibo foun rara.
Bi ẹnikan ba wa ti ọpọ ọmọ Naijiria gbagbọ pe o n da nnkan pọ pẹlu awọn agbesunmọmi ati ajinigbe, Sheikh ilu Kaduna nni, Ahmad Gumi, ni.
Titi di asiko yii ni ẹnu ṣi n kun Aafaa naa, bo tilẹ jẹ pe Gumi ko yee sọ pe oun ko mọ nnkan kan nipa awọn agbebọn ju pe oun ko fẹ kijọba fi agidi ba won lo lọ.
Ijọba ilẹ Saudi Arabia paapaa le Gumi pada lasiko to fẹ ṣiṣẹ Hajj lọdun to kọja, lori ọrọ dida nnkan pọ pẹlu awon agbesunmọmi yii naa ni.
Bi eeyan ba wa n ṣe ọrẹ ẹni ti ọpọ araalu ko yọnu si, oju iru ẹni naa ni wọn yoo fi maa wo ẹni ti wọn ba ri pẹlu rẹ
Eyi ni ohun to n ṣẹlẹ si gbajumọ sọrọsọrọ to fẹ dupo gomina ipinlẹ Oyo ni 2027, Alhaji Oriyomi Hamzat bayii.
Ẹni ti ẹnu ti n kun tipẹ pe ọrẹ Sheihk Gumi ni, ati pe iwajọwa lo n jẹ ọrẹjọrẹ ni ọrọ awọn mejeeji.
Loootọ lo ti pẹ ti ẹnu ti maa n kun Oriyomi Hamzat pẹlu iwa ati iṣe rẹ, paapaa julọ nipa jijẹ alakatakiti ẹsin Islam.
Ọpọ eeyan lo gbagbọ pe bi Gumi ṣe jẹ alakatakiti ẹsin Islam ni Oriyomi naa jẹ bẹẹ pẹlu.
Afiwe ti wọn maa n ṣe fun eyi ni pe Gumi wa sibi eto kan ni yunifasiti ilu Ibadan, Oriyomi Hamzat naa si wa nibẹ pẹlu bi wọn ṣe maa n fi ẹsun naa kan an.
Awọn kan tilẹ sọ pe Oriyomi lo pe Gumi wa, ati pe nitori rẹ ni wọn ṣe jọ jokoo ti ara wọn nibi eto naa.
Ṣaaju lo ti jẹ pe Oriyomi ko tako eyi, fidio kan si wa ti sọrọsọrọ ori redio naa ti n sọ pe Gumi ki I ṣe ọdaran, nitori ijọba apapọ ko pe bẹẹ, wọn ko si sọ pe o ṣe awọn lẹṣẹ kankan.
Ṣugbọn ni lasiko yii ti Oriyomi n gbiyanju lati di gomina ipinlẹ Oyo lodun to n bọ, labẹ akọmọna rẹ ti I ṣe 'Oyo n pe ọ, ọpọ ẹnu ti bẹrẹ si I kun un ju ti tẹlẹ lọ lori ajọṣepọ rẹ pẹlu Gumi to wọ Ibadan wa ṣeto, ati lorii pe ọta Kristẹni, ọrẹ Gumi ni Oriyomi n ṣe.
Lati fọ orukọ ara rẹ mọ, ati kawọn eeyan ma baa maa pe awọn ọmọ rẹ ni 'Bandiiti, ọmọ ọrẹ Gumi' ni Oriyomi ṣe fi fidio kan sita bayii, nibi to ti sọ ọpọ ọrọ lori ohun ti aye gbagbọ nipa rẹ.
"Mi o ri Gumi ri laye mi, emi kọ ni wọn ri nibi eto ti Gumi ṣe ni Yunifasiti Ibadan.
"Emi gan-an maa n ba wọn bu Gumi lọpọ igba ni, mo maa n beere pe ki lo de ti ijọba apapọ ko ṣe mu un.
"Emi kọ ni mo gbe Gumi wa si Yunifasiti Ibadan, emi si kọ ni wọn ri ninu fọto ti wọn ya nibẹ, ẹni yẹn de fila bii temi ni, emi kọ.
"Ọjọ ti Gumi wa si UI, emi o si nibẹ, ileeṣẹ wa lo wa nibẹ. "Bawo lawọn eeyan ṣe wa n sọ pe emi ni mo gbe e wa si Yunifasiti Ibadan.
"Ẹ ni kawon to ba n sọ pe mo mọ Gumi mu ẹri wa o, tori mi o ni I gba,mo maa gbe igbesẹ lori ọrọ yii.
"Wọn ni ki n ma dahun, ki n ma sọrọ, nitori awon ọmọ mi ni mo ṣe jade sọrọ yii, ki wọn le rin lawujọ. Ko ma di pe ti won ba da orukọ wọn ti won fi Oriyomi Hamzat si, won
📌 Kaynak
Bu özet BBC Yoruba kaynağından otomatik derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.
Orijinal haberi oku →