Wo kókó ohun mọ́kànlá tí Tinubu fi ránṣẹ́ sọ́mọ Náíjíríà lórí ààbò àti ọrọ̀ ajé láti sàmì ọdún kẹta rẹ̀ nípò ààrẹ

📌 Diğer 📰 BBC Yoruba 🕐 29.05.2026
Wo kókó ohun mọ́kànlá tí Tinubu fi ránṣẹ́ sọ́mọ Náíjíríà lórí ààbò àti ọrọ̀ ajé láti sàmì ọdún kẹta rẹ̀ nípò ààrẹ

Aarẹ Bola Tinubu ni yiyọ owo iranwọ ori epo, riro owo naira lagbara lọja agbaye ati gbigbe ogun ti aabo to mẹhẹ ti oun dawọle, ti so eso rere.

Ọjọ Ẹti, ọjọ kọkandinlọgbọn oṣu Karun-un ọdun 2026 yii lo pe ọdun mẹta ti Bola Tinubu ti wa nipo aarẹ orilẹede Naijiria.

Layajọ ọdun kẹta naa, Tinubu fi atẹjade kan sita lati ọwọ olukede rẹ, Bayo Onanuga.

Ninu atẹjade naa ni Aarẹ ti ni gbogbo awọn igbesẹ bii yiyọ owo iranwọ ori epo (fuel subsidy removal), riro owo naira lagbara lọja agbaye, gbigbe ogun ti ai si aabo ati bẹẹ bẹẹ lọ toun da wọle ti so eso rere fun orilẹede yii.

Labala ọrọ aje ati idagbasoke, Aarẹ Tinubu sọ pe o ti han kedere pe ilọsiwaju ti ba ọrọ aje Naijiria, o si ti le figa gbaga pẹlu awọn akẹgbẹ rẹ ju bo ṣe wa ni 2023 toun gbajọba lọ.

Aarẹ ṣalaye pe awọn to fẹ da ileeṣẹ silẹ ni Naijiria ti n ni igbagbọ ninu rẹ ju ti tẹlẹ lọ, ọjọ ipin idokowo n ṣe daadaa, bẹẹ ni awọn ileeṣẹ ti n jere ju ti tẹlẹ lọ ni Tinubu sọ.

Awọn ọna marosẹ to din diẹ lẹgbẹrun mẹta (2700) ni iṣakoso Tinubu ti ṣe bo ṣe sọ.

Awọn ọna bii Lagos-Calabar Coastal Highway, Sokoto-Badagry Super Highway, Abuja-Kaduna-Zaria-Kano Road ati bẹẹ bẹẹ lọ.

Awọn eyi ti din wahala ọkọ ku bo ṣe wi, o si ti jẹ ki irinajo rọrun.

Aarẹ Tinubu sọ pe atunto to ba ẹka yii ti mu ọpọlọpọ biliọnu dọla waye fun Naijiria, pẹlu awon ileeṣẹ elepo ilẹ okeere ti wọn ti kọyin si Naijiria tẹlẹ, ṣugbọn ti wọn ti pada wa nigba ti iṣakoso oun ti gbe igbesẹ

Aarẹ sọ pe eto onibiliọnu marun-un dola ($5 billion NLNG Train) ti n pari lọ, ti yoo si jẹ ki epo rọbi pọ si I, ti Naijiria yoo ri lo, ta pupọ soke okun bo ṣe sọ.

'Gbese ni ẹka ina mọnamọna wa n jẹ tẹlẹ, wọn ko si mọ ibi ti wọn dojukọ. Lonii, a ti n tako awọn iṣoro yẹn.

"A mọ pe ko si orilẹeede to le goke agba ninu okunkun, la ṣe n kowo le ilana ọna ọba ti yoo ran awọn ileeṣẹ ati okoowo lọwọ"

Aarẹ Tinubu sọ pe ẹgbẹlẹgbẹ awọn agbẹ ni iṣakoso oun ti ro lagbara pẹlu nnkan ọgbin, ajilẹ, ẹrọ igbalode ati bi wọn yoo ṣe ko ire oko wọn de ọja lati ta.

Ilana ẹyawo ti wọn gbe kalẹ fun awọn akẹkọọ ile ẹkọ giga (Nigerian Education Loan Fund) ni Aarẹ sọ pe o ti fun akẹkọọ to le ni 1.5million ni anfaani lati le kawe nile ẹkọ giga.

O ni owo to le ni ₦282 ni ijọba oun ti lo lati ri I pe ko si akẹkọọ to ni iṣoro lati wa nile ẹkọ giga nitori ai si owo.

"Eto ireti ọtun nipa ile gbigbe (Renewed Hope Housing Programme), pẹlu ti ijọba apapọ Federal Housing Authority (FHA), n pese ile to le ni ẹgbẹrun mẹwaa (10,000 housing units) kaakiri ipinlẹ mẹrinla ati ilu Abuja ni Aarẹ Tinubu wi.

Ẹgbẹẹgbẹrun awọn ile iwosan ijọba alabọọde kaakiri ni wọn ti ro lagbara bi Tinubu ṣe ṣalaye, bẹẹ si ni eto ilera ma-da-mi-dofo naa tun wa fawọn ọmọ Naijiria to n ṣe alaini.

Owo ounjẹ to lọ silẹ lati 2023 si 2024 yoo maa lọ bẹẹ bi A

📌 Kaynak

Bu özet BBC Yoruba kaynağından otomatik derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.

Orijinal haberi oku →
← Tüm haberlere dön