Ìtàn mánigbàgbé: Bí ilà kíkọ ṣe bẹ̀rẹ̀ nílẹ̀ Yorùbá àti bí wọn ṣe fi ilà kíkọ kó ìlú kan lógun

📌 Diğer 📰 BBC Yoruba 🕐 29.05.2026
Ìtàn mánigbàgbé: Bí ilà kíkọ ṣe bẹ̀rẹ̀ nílẹ̀ Yorùbá àti bí wọn ṣe fi ilà kíkọ kó ìlú kan lógun

BBC News Yorùbá ṣe wọ inú ìtàn lọ, láti ṣe ilanilọyẹ lórí ohun tó fà á, tí ìran Yoruba ṣe ń kọ ila àti bí wọn ṣe fi ilà kíkọ kó ìlú kan lógun.

Ní ilẹ Yoruba, ila kíkọ jẹ ohun pàtàkì láyé àtijọ́ torí ó ń jẹ ka dá àwọn èèyàn ìlú kan tàbí ẹbi kan mọ yàtọ̀ sí òmíràn.

Bi o tilẹ jẹ pe ọ̀pọ̀ ìlú àti ẹbi ni kò fi bẹẹ kọ ila mọ lóde òní àmọ́ anfaani ila kíkọ láyé àtijọ́ kii se kékeré.

Lásìkò yìí, ọ̀pọ̀ ọmọ Kaarọ Oojire ni ko mọ ìtàn tó rọ̀ mọ́ ila kíkọ àti bó ṣe bẹ̀rẹ̀.

Ìdí rèé tí BBC News Yorùbá ṣe wọ inú ìtàn lọ, láti ṣe ilanilọyẹ lórí ohun tó fà á, tí ìran Yoruba ṣe ń kọ ila.

Bákan náà, a tún mọ ọna ti wọn gba fi ogún ja ìlú kan, ko ìlú kan lẹru torí ilà kíkọ.

Gẹ́gẹ́ bi ìtàn ṣe fi yẹ wá látinú ìwé ìtàn nípa ilẹ Yoruba ti Àlùfáà Samuel Johnson kọ, aye Alaafin Sango nilu Oyo ni ìtàn ila kíkọ ti bẹ̀rẹ̀.

Gẹ́gẹ́ bí a ti gbọ́, Sango jẹ ọmọ bibi inú Oranmiyan tíì ṣe ọmọ Okanbi to jẹ ọmọ Oduduwa tíì ṣe ẹni to ṣẹ ìran Yoruba silẹ.

Lara awọn ọmọ Oranmiyan ni Sango àti Ajaka, tíí ṣe Aláàfin kẹrin nilu Oyo, to jẹ ìlú to tóbi, tó sì ń ṣe akoso ilẹ̀ Yorùbá lapapọ.

Sango jẹ alágbára tí kò gbà gbẹrẹ, ó ní ẹ̀rù lára pupọ, ó sì máa ń yọ èéfín àti iná ni ẹnu èyí tó mú káwọn èèyàn bẹru rẹ pupọ.

Bákan náà, ọba ìlú Òwu, tí a mọ̀ sí Olowu náà lágbára pupọ, kódà ju ọba Ọ̀yọ́ lọ nígbà náà,

Bi Oranmiyan to tẹ ìlú Oyo do sì ṣe wàjà, tí Ajaka jọba, ní Olowu pàṣẹ fáwọn èèyàn ìlú Oyo láti máa san isakọlẹ fún òun.

Aláàfin Ajaka jẹ ọba oníwà tútù bíi àdàbà, isakọlẹ to gba láti san fún Olowu sì ló mú káwọn èèyàn ìlú Oyo ṣe rọ ọ lóye Aláàfin.

Lẹyin rẹ ni wọn fi Sango jẹ Aláàfin, ó sì jẹ ọmọdé, bẹ́ẹ̀ ni Olowu tún fẹ rẹ ẹ jẹ torí pé ọmọdé ni.

Àmọ́ Ata kéré, ìjà jù ú ní Aláàfin Sango, bí Olowu ṣe tún pàṣẹ fún un láti máa san isakọlẹ fún òun, ní Aláàfin Sango fọnmú.

Sango ni láéláé, òun kọ́ lè forí balẹ̀ fún Olowu tàbí kí òun sìn-ín, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olowu dunkooko láti kó aya àtàwọn ọmọ rẹ ni ẹrú.

Lẹyin ó rẹyìn, ìjà ńlá bẹ silẹ nílùú Oyo laarin Olowu àti Aláàfin Sango, Olowu sì kó ogun wọ ìlú Oyo.

Sango àfihàn agbára rẹ, o dúró bíi Akọni to jẹ, ọ̀pọ̀ èéfín àti iná ń yọ ní ẹnu àti ihò imú rẹ èyí tó lágbára pupọ.

Wọn ni bí ọmọdé bá dé ibi ẹ̀rù, ẹ̀rù yóò bá a, jinni-jinni bo Olowu atawọn ọmọ-ogun rẹ, ṣe ni wọn fojú ìjà silẹ, wọn salọ kúrò lójú ogún.

Lẹyin èyí, Sango já ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun, ó sì ṣẹgun, ó di ẹrú jẹjẹ tí gbogbo èèyàn ń bẹru rẹ, o si di Aláàfin tí ẹnikẹni kò le gbe iná woju rẹ.

Láyé ìgbà náà, ìlú Òkò ni ibujoko ìjọba Oyo, èyí tí wọn ń pè ní Ọ̀yọ́korò lásìkò náà, tí Aláàfin Sango sì ń gbìyànjú láti kó ibujoko ìjọba wá sí Ọyọ.

Lọ́nà àti mú àfojúsùn rẹ yìí ṣẹ, Sango fẹ́ rúbọ ní ojú orori ìyá rẹ àmọ́ kò mọ orúkọ ìyá rẹ mọ torí pé ọmọ ọwọ́ lo wa nígbà tí ìyà rẹ kú.

Iya Sango jẹ ọmọọba Elempe tíì ṣe ọba Nupe tí a t

📌 Kaynak

Bu özet BBC Yoruba kaynağından otomatik derlenmiştir. Tamamı için orijinal habere gidin.

Orijinal haberi oku →
← Tüm haberlere dön